Alága ilé iṣẹ́ ètò ààbò kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tantita ní ìpínlẹ̀ Delta; Ekpemupolo tí ìnagijẹ rẹ̀ ń jẹ́ Tompolo ti sọ̀rọ̀ lórí ìgbàgbọ́ àti ìrètí rẹ̀ nínú ìṣèjọba Bola Ahmed Tinubu.
Tompolo wí pé ẹni tó bạ mọ̀nà náà ló yẹ ká tẹ̀lé, kò sì sí ẹni méjì tó mojú Ògún Nàìjíríà lásìkò yìí ju Ààrẹ Bola Tinubu lọ. Ó wí pé digbí ni òun wà lẹ́yìn Tinubu tí òun sì ní ìgbẹ́kèlé nínú rẹ̀ pé òun ni yóò mú orílẹ̀-ede Nàìjíríà dé ilẹ̀ ìlérí.
Bí a bá pa obì, a ó yọ abidun ni, èyí ló mú kí Tompolo ó ṣe àlàyé àwọn àṣeyọrí tí ikọ̀ Tantita ti ṣe lábẹ́ ìjọba Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu. Ó wí pé ikọ̀ Tantita náà ti ṣẹ́gun àwọn tí wọ́n máa ń bẹ́ ọ̀pá epo rọ̀bì dé ààyè tó lápẹẹrẹ.
Lọ́gán tí àwọn bá sì ṣẹ́gun èyí láṣẹ̀ẹ́wọlẹ̀ ni ọrọ̀ ajé Nàìjíríà yóò tún gbèrú síi látàrí pé èyí tí àwọn tó ń bẹ́ ọ̀pá epo ń jí náà yóò kúrò níbẹ̀.
Tompolo ṣe ìlérí wí pé ìbò mílíọ́nù mẹ́wàá ni òun yóò fi jíṣẹ́ nínú ètò ìdìbò ààrẹ ọdún 2027.
Ọ̀rọ̀ Tompolo yìí dà bí ìkínlẹ́yìn fún ọ̀rọ̀ tí Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu ti fúnra rẹ̀ sọ tẹ́lẹ̀ ṣáájú àsìkò yìí lọ́jọ́ tó ṣe ayẹyẹ ọdún kejì lọrí ipò.
Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu sọ̀rọ̀ lọ́jọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n, oṣù Èbìbí tó jẹ́ àyájọ́ ọdún kejì tó dé ipò ààrẹ. Ó wí pé ohun tí òun fi gbogbo ọdún méjì náà ṣe ni láti ṣètò ìpìlẹ̀ rere, ìpìlẹ̀ tó níkìmí fún ọjọ́ iwájú Nàìjíríà.
Ààrẹ wí pé ìjọba òun ti ṣètò ìgbé ayé ìrọ̀rùn, ètò ọrọ̀ ajé tó yè koro àti àtìlẹ́yìn fún àwọn ọmọ orílẹ̀-ède Nàìjíríà. Iṣẹ́ ìdàgbàsókè àti ìpìlẹ̀ rere náà ń tẹ̀síwájú.
Tẹrú tọmọ ti gbogbo mùtúmùwà ni yóò máa gbádùn bíi èèrà inú ṣúgà nígbà tí gbogbo rẹ̀ bá délẹ̀ tán.
Ẹ̀yin náà ṣá mọ̀ pé ìkòko tí yóò bá játa, dandan ni kí ìdí rẹ̀ ó gbóná, ààrẹ ò sùn bẹ́ẹ̀ sì ni kò wo lórí bí orílẹ̀-ède Nàìjíríà ó ṣe dùn yùngbà yùngbà. Èyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí ààrẹ sọ.
Bákan náà ni ààrẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọmọ orílẹ̀-ède Nàìíríà fún ìfọwọ́sowọ́pọ̀ àti àtìlẹ́yìn wọn, ó wí pé kò sí ohun tí òun le dá ṣe bí ẹ kò bá ṣe àtìlẹ́yìn fún òun. Ààrẹ wí pé kí ẹ dúró ṣinṣin nínú ìgbàgbọ́, kí ẹ má ṣe mikàn tàbí ṣiyè méjì nípa ìṣejọba òun, ìrọ̀rùn igi ni ìrọ̀rùn ẹyẹ, ìgbàgbọ́ yín ni ó le mú kí òun ó ṣe àṣeyọrí.
Ọ̀rọ̀ ààrẹ tẹ̀síwájú pé òun mọ rírí sùúrù àti ẹ̀mí ìfaradà tí ẹ ní lásìkò yìí, ó wí pé kí ẹ mọ̀ dájú pé gbogbo rẹ̀ ni yóò dẹ̀rọ̀ pẹ̀sẹ̀ pẹ̀sẹ̀ láìpẹ́ jọjọ. Ààrẹ wí pé orílẹ̀-ède Nàìjíríà tí kò ní jẹ gbèsè sí ilé ìfowópamọ́ àgbáyé tàbí jẹ orílẹ̀-èdè kankan lówó tí yóò sì le dá gbọ́ bùkátà ara rẹ̀, pàápàá tí owó Náírà yóò gbera sọ tí yóò sì níyì ju owó òkè òkun lọ ni òun ń kọ́ lọ́wọ́ báyìí, nígbà tí òun bá sì ṣetán, gbogbo yín lẹ ó máa jó mùkúlú mùkẹ.
Lẹ́yìn gbogbo ọ̀rọ̀ yìí, kò le ya ni lẹ́nu bí àwọn èèyàn bá ṣe àtìlẹyìn fún ààrẹ lórí ìdìbò ọdún 2027. Kódà, kìí ṣe Tompolo nìkan ló fi àtìlẹyìn rẹ̀ hàn, Gómìnà ìpínlẹ̀ Kogi; Ahmed Ododo náà ní ìgbàgbọ́ nínú ìṣejọba ààrẹ Bola Ahmed Tinubu. Ìròyìjn tirẹ̀ kà báyií pé:
Gómìnà ìpinlẹ̀ Kogi; Ahmed Ododo kí ààrẹ Bola Ahmed Tinubu kú oríire àyájọ́ ọdún kejì lórí ipò. Ó wí pé ọlá àbàtà níí módò ó ṣàn, ọlá baba lọmọ fi ń yan; bí kò bá sí ti ààrẹ Bola Ahmed Tinubu ni, ibo ni àwọn ọmọ Nàìjíríà ò bá gbé ọ̀rọ̀ wọn gbà ní orílẹ̀-èdè tó ti dẹnu kọlẹ̀ tán kí baba tó bọ́ sípò.
Ododo wí pé ààrẹ Tinubu ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn iṣẹ́ àtúntò ní èyí tó mú kí ìgbé ayé ó rọrùn fún àwọn ọmọ orílẹ̀-ède Nàìjíríà, ó ṣe àpèjúwe Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu gẹ́gẹ́ bíi aṣáájú tó ní ètò àti àlàkalẹ̀.
Ọ̀rọ̀ Ododo tẹ̀síwájú pé àsìkò tí a wà yìí ni àsìkò ìkórè, èso iṣẹ́ takuntakun tí ààrẹ fi ọdún méjì àkọ́kọ́ náà ṣe ti ń délẹ̀ báyìí, kí a máa jẹ iṣẹ́ rere tí baba ṣe fún wa ló kù báyìí.
Ẹni tí yóò parọ́ ni yóò wí pé ẹlẹ́rìí òun wà ní ọ̀run, àwọn tó gbẹ̀rí ààrẹ Bola Ahmed Tinubu jẹ́ lórí ìlérí rẹ̀ yìí pọ̀ díẹ̀, yàtọ̀ sí Gómìnà Ahmed Ododo àti Tompolo tí a ti mẹ́nubà lókè yìí, ààrẹ àná; Muhammadu Buhari náà ṣègbè lẹ́yìn Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu pé kí ẹ má fi ti ọ̀rọ̀ àwọn olóṣèlú alátakò ṣe nítorí pé ariwo ọjà lásán ni wọ́n, bẹ́ẹ̀ má sì ni kí ẹ má retí kí gbogbo rẹ̀ ó dẹ̀rọ̀ lẹ́kan náà nítorí pé ọjọ́ tí a bá gbin iṣu kọ́ ni yóò ta.
Ọ̀rọ̀ Buhari tẹ̀síwájú pé ààrẹ Tinubu gbé ogun ti ìṣẹ́ àti òṣì ó sì ti ń nípa rere, ẹ fún un ní àǹfààní àti parí iṣẹ́ rere tó dáwọ́lé yìí kí ẹ le jọrọ̀ ibẹ̀.
Àsìkò yìí ni ẹgbẹ́ òṣèlú APC nílò àtìlẹyìn yín jùlọ, láti gbé ààrẹ Bola Ahmed Tinubu wọlé lẹ́ẹ̀kejì kí ó le máa bá iṣẹ́ rere lọ.
Pẹ̀lú gbogbo atótónu yìí, ó han gbangba gbàǹgbà pé Ìlúfẹ́milóyè ni Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu, tẹrú tọmọ ló ń gbádùn ìṣejọba rẹ̀ tí wọ́n sì ń kọrin pé;
Tinubu máa báṣẹ́ rẹ lọ
Iṣẹ́ rẹ̀ mà ń tẹ́ wa lọ́rùn —–
Discussion about this post