Mínísítà fún ètò ìlera ilẹ̀ wa; Iziaq Salako kọminú lórí ipò tí ètò ìlera ilẹ̀ wa wà báyìí nípa pé gbogbo àwọn akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ dọ́kítà ló ti jápa tán lọ sí òkè òkun.
Ó wí pé ní ilé ìwòsàn nísìn yìí, dọ́kítà kan ṣoṣo ni ó ń tọ́jú aláìsàn tí iye wọn lé ní ọ́dúnrún.
Salako sọ ọ̀rọ̀ yìí níbi àpérò kan tó wáyé ní Abuja lọ́jọ́ Ajé, ó wí pé àdójúkọ ńlá ti dé bá ètò ìlera nípa pé gbogbo àwọn dọ́kítà ló ti sá lọ sí òkè òkun tán látàrí pé iṣẹ́ náà tà lọ́hùn-ún.
Àpérò yìí wáyé lẹ́yìn tí Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu pàṣẹ kí àwọn dọ́kítà ó padà sí ẹnu iṣẹ́ kíá.
Àwọn dọ́kítà gùn lé ìyanṣẹ́lódì láti ọjọ́ Àbámẹ́ta lórí pé ìjọba ń fi ẹ̀tọ́ wọn dùn wọ́n, wọ́n wí pé àwọn kò rí owọ́ oṣù gbà lásìkò tó yẹ, àjẹmọ́nú kò jáde, wọn kò rí irin iṣẹ́ lò bẹ́ẹ̀ sì ni gbogbo ilé ìwòsàn kò ṣeé rí.
Salako wí pé bí àwọn dọ́kítà ti jápa yìí kò tilẹ̀ burú tó pé àwọn kò rí àwọn mìíràn gbà sí iṣẹ́, lọ́gán tí wọ́n bá ti kẹ́kọ̀ọ́jáde báyìí, òkè òkun ni wọ́n ń lọ, èyí gan-an ló fà á tí àwọn ilé ìwòsàn kò fi ní dọ́kítà.
Ó fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé kìí ṣe orílẹ̀-ède Nàìjíríà nìkan ló ní àdojúkọ yìí, ó kàn jẹ́ pé ọrọ̀ ajé tó dẹnukọlẹ̀ ló jẹ́ kí ó burú ní Nàìjíríà àmọ́ ìjọba ti bẹ̀rẹ̀ gbogbo ètò láti dá ohun gbogbo padà sípò.
Lára ohun tí ìjọba ń ṣe ni kíkọ́ àwọn ilé ẹ̀kọ́ ẹ̀kọ́ṣẹ́ òògùn òyìnbó kún èyí tó ti wà nílẹ̀ wọn yóò sì rọ àwọn ọ̀dọ́ láti wá kẹ́kọ̀ọ́ ìṣègùn òyìnbó bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé yóò gba àkókò díẹ̀ kó tó le so èso rere nítorí pé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà yóò kẹ́kọ̀ọ́gboyè ná kí wọ́n tó le dí àlàfo yií.
Àwọn orílẹ̀́-èdè kan tilẹ̀ ti fi òfin de àwọn dọ́kítà àti oníṣẹ́ ìlera tí wọn kò ní le kúrò ní orílẹ̀-ède wọn , àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀ láìpẹ́ kí a le tọ́jú àwọn yòókù sílùú.
Bákan náà ni Salako ṣe àlàyé ìdí tí àwọn ilé ìwòsàn ìjọba fi ń gba àwọn dọ́kítà fìdí-hẹ́ lásìkò yìí, ó wí pé ojoojúmọ́ ni àwọn ojúlówọ́ dọ́kítà ń fìṣẹ́ sílẹ̀, ètò ìgbanisíṣẹ́ ìjọba sì gùn, láti orí ìdánwò dé orí àyẹ̀wò àti ìfọwọ́sí, èyí kò ṣe é ṣe lásìkò yìí ni àwón ṣe fún àwọn dọ́kítà àgbà láṣẹ́ àtigba dọ́kítà fìdí-hẹ́ ná kí gbogo nǹkan ó fi bọ́ sípò.
Níbi àpérò yìí náà ni àjọ àwọn òṣìṣẹ́ ìlera ti sọ̀rọ̀ fún gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ ìlera pé ìyà ni ìjọba fi ń jẹ wọ́n lójú méjéèjì, láti ibi owó oṣù, àjẹmọ́nú tó fi dé orí ọrọ̀ ajé tó dẹnu kọlẹ̀, ìyà ló bá dé fún wọn.
Níbi àpérò kan tó wáyé ní Abuja ni àjọ yìí ti sọ̀rọ̀. Alága àjọ náà; Kabiru Sani àti akọ̀wé gbobogbò; Auwalu Kiwaya ló tẹ́ pẹpẹ ọ̀rọ̀ náà.
Wọ́n wí pé gbogbo àwọn akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ dọ́kítà, nọ́ọ̀sì tó fi dé orí àwọn amojúẹ̀rọ àyẹ̀wò ló ti bá kó le dáa lọ sí òkè òkun.
Ètò ìlera yìí ti burú ju ohun tó yẹ lọ, ó jìnnà réré sí ètò ìlera fún èèyàn, gbogbo ilé ìwòsàn ti dẹnukọlẹ̀, kò sí ibùsùn fún aláìsàn, kò sí owó oṣù gidi fún òṣìṣẹ́, kò sí òògùn, gbogbo rẹ̀ ló polúkúrúmusu.
Àsìkò ti tó fún ìjọba láti gbé ìgbésẹ̀ lórí èyí ní kíákíá láti dá ohun gbogbo padà sípò.
Nínú oṣù Ògún ni ààrẹ rọ gbogbo àwọn tó jápa láti darí wálé pé Nàìjíríà ti dára.
A mú ìròyìn náà wá pé:
Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti rọ àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè yìí tí wọ́n jápa lọ sí òkè òkun pé kí wọn darí wálé, àjò kìí dùn bí ilé àti wí pé ilé náà làbọ̀ ìsinmi oko.
Ó wí pé orílẹ-èdè Nàìjíríà ti kúrò ní bí wọ́n ṣe fi sí nígbà tí wọ́n jápa lọ sí òkè òkun, Nàìjíríà ti dára gan-an ni ó sì tún ti gòkè àgbà báyìí.
Ààrẹ sọ èyí níbi àpéjọ àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó wà ní Yokohama, Japan.
Olùbádámọ̀ràn ààrẹ lórí ìfitónilétí; Bayo Onanuga ló bu ọwọ́ lu àtẹ̀jáde yìí, nínú rẹ̀ la ti kà á pé ìṣèjọba Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu ti ṣe àtúnṣe sí ọrọ̀ ajé tó mẹ́hẹ ṣáájú kí ó tó gorí ipò, ó sì ń ṣiṣẹ́ lórí àwọn àtúnṣe tí yóò pèsè iṣẹ́ lọ́pọ̀ yanturu, òkòwò ati àwọn ohun amáyédẹrùn.
Ọ̀rọ̀ ààrẹ Bola Ahmed Tinubu tẹ̀síwájú pé ‘Inú mi dùn láti ríi pé àwọn ọmọ Nàìjíríà kọ̀ọ̀kan ti ń darí wálé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn kan takú sí òkè òkun, a kò le fi ipá gbé wọn wálé nítorí pé òfin fi ààyè gba kí èèyàn ó gbé ibi tó wù ú.
Àmọ́ mo rọ̀ yín, nítorí ọrọ̀ ajé àti ìdàgbàsókè Nàìjíríà, ẹ má takú sí òkè òkun, ẹ padà wá sílé.
Bí ẹ bá kọ̀ látì wá kó ipa yín nínú ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè yín, ta ni yóò bá a yín ṣe é?
Ìṣèjọba mi ti pèsè ètò ìlera tó péye láti dẹ́kun lílọ gba ìtọ́jú lókè òkun bẹ́ẹ̀ sì ni ọrọ̀ ajé ti fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin.
Ẹ kò le dá ìdàgbàsókè ìlú dá ìjọba nìkan, ẹ máa bọ̀ nílé kí ẹ wá kópa, ẹ fi ẹnu rere sọ ọ̀rọ̀ Nàìjíríà.
Bí ẹ bá takú sí òkè òkun tí ẹ kò bá wálé wá kópa nínú ìṣèjọba yìí, á jẹ́ pé a kùnà nínú adarí ọjọ́ ọ̀la tí a ní a ń tọ́’ èyí ni àwọn ohun tí ààrẹ sọ.
Lẹ́yìn tí ààrẹ gúnlẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀ ló ké sí Mínísítà fún ìdásílẹ̀ àti àmójútó àwọn ilé iṣẹ́; Aṣòfin John Enoh àti igbákejì alága ẹ̀ka ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ àti àwọn ohun amáyédẹrùn; Khalil Suleiman Halilu láti ṣe àlàyé ibi tí ààrẹ Bola Ahmed Tinubu bá iṣẹ́ ìdàgbàsókè Nàìjíríà dé.
Gbogbo bí ìlú ó ṣe dáa náà ni ààrẹ ń ṣe kí àwọn èèyàn ó ba má jápa mọ́.




