Gbajúgbajà òǹkọ̀wé Chimamanda Ngozi Adichie ti fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn Euracare tó wá ní Èkó pé wọ́n fi àìbìkítà wọn gba ẹ̀mí ọmọ rẹ̀, ọmọ kékéré tó ń lọ pé ọdún méjì.
Ngozi ṣe àlàyé pé àwọn wá ṣe ọdún kérésì ní Èkó ni ọmọ náà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Nkanu bẹ̀rẹ̀ àìsàn, wọ́n kọ́ rò pé otútù ni àmọ́ àyẹ̀wò nílé ìwòsàn fi hàn pé àwọn kòkòrò àìfojúrí ló fà á, wọ́n ṣètò àti gbé e lọ sí orílẹ̀-ède United Kingdom fún ìtọ́jú, gbogbo ètò ti tò àmọ́ àwọn dọ́kítà lọ́hùn-ún bèèrè fún àwọn àyẹ̀wò kan kí ó tó lọ sí ọ̀hún.
Ó ku ọ̀la tó máa lọ sí UK ni wọ́n gbé e lọ sí ilé ìwòsàn Euracare fún àwọn àyẹ̀wò ara náà. Àyẹ̀wò náà gba kí ọmọ náà ó wọ inú ẹ̀rọ wọn kò sì fẹ́ kí ó mira, wọ́n sọ fún ìyá rẹ̀ pé àwọn yóò pa iyè Nkanu ní ráńpẹ́ kí ó má baà mira nínú ẹ̀rọ náà, nígbà tó yá ni dọ́kítà gbé e ní pàjáwìrì lọ sí ẹ̀ka pàjáwìrì tí àwọn nọ́ọ̀sì sì ń sáré kiri, ìgbà náà ni Ngozi mọ̀ pé nǹkan ti yíwọ́.
Ngozi ní dọ́kítà tó kun ọmọ náà lóorun fún un ní àpọ̀jù òògun apaniníyè tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní propofol wọn kò tún yẹ ọmọ náà wò títí tó fi di pé èémí rẹ̀ lọ sílẹ̀.
Wọ́n de ẹ̀rọ ìmí mọ́ ọn nímú, wọ́n sì gbìyànjú àti jíi sáyé. Ọmọ náà jí sáyé padà ó sì nílò àti lọ sí yàrá pàjáwìrì. Ngozi ní dọ́kítà náà yọ ẹ̀rọ tí ọmọ náà fi ń mí ó sì gbé e lé èjìká láti yàrá iṣẹ́ abẹ lọ sí yàrá pàjáwìrì, nígbà tí yóò fi dé ibẹ̀, èémí rẹ̀ ti lọ sílẹ́ pátápátá, ara rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní sẹ́ gìrì ọkàn rẹ̀ sì da iṣẹ́ sílẹ̀. Bí ọmọ náà ṣe kú nìyẹn.
Ngozi Adichie fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn Euracare pé wọ́n fún ọmọ òun ní àpọ̀jù òògun propofol wọn kò sì tún yẹ ọmọ náà wò, nígbà tó tún jí sáyé, dọ́kítà náà tún yọ ẹ̀rọ èémí nímú rẹ̀ ó sì gbé e bẹ́ẹ̀ lọ sí yàrá pàjáwìrì. Ngozi ní ìwà ọ̀daràn gbáà ni dọ́kítà náà hù.
Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tẹ̀síwájú pé àwọn èèyàn méjì ló ti fi ẹjọ́ sùn báyìí nípa dọ́kítà kan náà, wọ́n ní bí ó ṣe máa ń fún àwọn ọmọdé ní àpọ̀jù òògùn nìyẹn, kìí ṣe ti Nkanu làkọ́kọ́.
Ngozi bèèrè ìdí tí ilé ìwòsàn Euracare fi gbà á láàyè láti máa ṣiṣẹ́ lọ? Ó ṣe ìlèrí láti fa ẹjọ́ náà, ó ní òun yóò ríi dájú pé ọmọ mìíràn kò ṣe àgbákò dọ́kítà yìí.
Bí ẹ kò bá gbàgbé, arákùnrin kan náà ti fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn aládàáni As-Salam Convalescent pé wọ́n fi ìwà àìbìkítà pa ìyàwó òun tó fẹ́ bímọ́.
Arábìnrin Kemi Akinbobola ti kú pẹ̀lú oyún nínú látàrí pé kò ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta náírà owó àsan-án-lẹ̀ tí ilé ìwòsàn bèèrè fún.
Ọjọ́ burúkú èṣù gbomi mu ni ọjọ́ náà jẹ́ fún ìdílé Akinbobola nígbà tí Kemi ń rọbí, ipò rẹ̀ burú díẹ̀ ó sì nílò ìtọ́jú pàjáwìrí àmọ́ ilé ìwòsàn aládàáni kan tí wọ́n gbé e lọ kọ̀ láti tọ́jú rẹ̀ nítorí pé ọkọ rẹ̀; Folajimi Akinbobola kò ní owó àkọ́san ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta náírà tí wọ́n ní kó san.
Dọ́kítà ilé ìwòsàn náà wí pé kí wọn ó máa gbé Kemi lọ sí ilé ìwòsàn ìjọba tó wà ní Epe láti Lekki, Kemi kò dé Epe tó fi dákẹ́.
Ọkọ rẹ̀ ló ká fọ́nrán bí Kemi ṣe wà nínú ìrora tó sì ń rọ́ ọ lójú. Folajimi fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn yìí pé àwọn ló ṣekú pa ìyàwó rẹ̀ nítorí pé wọ́n kọ̀ láti tọ́jú rẹ̀ nítorí owó.
Ilé ìwòsàn As Salam Convalescent tó wà ní Iwerekun, Ibeju-Lekki ní ìpínlẹ̀ Èkó náà fèsì sí ẹ̀sùn tí Akinbobola Folajimi fi kàn wọ́n lórí ìyàwó rẹ̀ tó kú.
Ẹ̀sùn tí Folajimi fi kan ilé ìwòsàn As Salam ni pé wọ́n kọ̀ láti tọ́jú ìyàwó rẹ̀; Kemi nígbà tí ó ń rọbí, ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta náírà ni Folajimi ní wọ́n bèèrè fún kí wọ́n tó tọ́jú rẹ̀, ojú ọ̀nà ilé ìwòsàn ìjọba Epe ni Kemi dákẹ́ sí.
Ẹni tó ni ilé ìwòsàn náà gangan; Ọ̀gbẹ́ni Rauf Salami ló bá àwọn akọ̀ròyìin sọ̀rọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà láàárọ̀ àná. Àlàyé tí Ọ̀gbẹ́ni Rauf ṣe tako ohun tí a gbọ́ láti ẹnu Akinbobola. Àlàyé náà lọ báyìí pé;
‘Lóòótọ́ ni wọ́n gbé Kemi wá sílé ìwòsàn wa lọ́jọ́ náà. Ipò tó wà burú jáì tó fi jẹ́ pé a kò le gbà á sọ́dọ̀ nítorí pé ó nílò kí ó gba ẹ̀jẹ̀ kó sì tún ṣe iṣẹ́ abẹ. A kò ní àwọn irin iṣẹ́ tí a le fi kojú irú ipò báyìí ni a fi ní kí ọkọ rẹ̀ ó máa gbé e lọ sí ilé ìwòsàn ìjọba Epe níbi tí wọn yóò ti le ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
Gbogbo ohun tí wọ́n lò ní ọ̀dọ wa kò tó ìṣẹ́jú mẹ́rin, a kò tilẹ̀ gbé e sọ̀ kalẹ̀ gan-an lórí kẹ̀kẹ́ tí wọ́n fi gbé e wá tí a fi ní kí wọ́n máa lọ sí Epe. Bí ba bá ní ká fún lómi, ó le kú sí ọ̀dọ wa nítorí pé kò sí ẹ̀jẹ̀ kankan lára rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni ẹ̀jẹ̀ kìí ṣẹ ohun tí a le rí lórí igbá bẹ́ẹ̀ yẹn, ìlànà wà tí a gbọdọ̀ tẹ̀lé.
ó ṣe pàtàkì láti fi kún un pé Kemi kò gba ìtọ́jú lọ́dọ̀ wa rí, ìgbà àkọ́kọ́ tí a ó ríi náà nìyẹn, a kò mọ nǹkan kan nípa ìlera rẹ̀ ṣaájú ọjọ́ náà ní èyí tí kò le jẹ́ kí a mọ bí a ṣe le tọ́jú rẹ̀ yàtọ̀ sí pé kò sí ẹ̀jẹ́ lára rẹ̀ mọ́. Mi ò lérò pé Kemi gba ìtọ́jú nílé ìwòsàn kankan nínú oyún náà nítorí pé kò sí àpẹẹrẹ pé ó gba ìtọ́jú aláboyún àti pé kò bá má burú tó bẹ́ẹ̀ yẹn bí ó bá ṣe pé àwọn ìtọ́jú kan ti wà lára rẹ̀ tẹ́lẹ̀.
Lórí ẹ̀sùn owó tí Folajimi ọkọ rẹ̀ fi kàn wá, irọ́ pátápátá ni, a kò tilẹ̀ sọ nǹkan kan nípa owó rárá, mi ò bá ní kí n fi ọlọ́pàá gbé e àmọ́ ó ṣẹ̀ṣẹ̀ pàdánù ìyàwò rẹ̀ ni àti pé Mùsùlùmí ni mí, mo fi gbogbo rẹ̀ lé Ọlọ́run lọ́wọ́’
Ẹ̀yin èèyàn wa, àlàyé tí Ọ̀gbẹ́ni Rauf ṣe rèé o, ó wí pé àwọn tí wọ́n ń lo ilé ìwòsàn náà déédéé le jẹ́ríì sí bí àwọn ṣe máa ń ṣe ìtọ́jú wọn tó.





