• About
  • Advertise
  • Careers
  • Contact
Tuesday, May 20, 2025
  • Login
  • Register
No Result
View All Result
NEWSLETTER
ÌWÉ ÌRÒYÌN YORÙBÁ
  • Ilé Wa
  • Ìròyìn
    • All
    • ijamba oko
    • Ìròyìn Agbègbè
    • Ọ̀rọ̀ Ààbò
    • Ọ̀rọ̀ ìdílé
    • Ọrọ̀-Ajé
    • Òṣèlú
    ÌJÀMBÁ INÁ LỌ́TÙN-ÚN LÓSÌ.

    ỌKỌ DÁNÁ SUN ÌYÀWÓ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ MẸ́TA NÍ ABIA.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒKÙNKÙN ṢEKÚ PA BENJAMIN NÍ IKORODU.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÌYÀWÓ NI OLAMIDE FẸ́ FỌ́ IRIN MỌ́ LÓRÍ TÓ FI BA ỌMỌ RẸ̀, ỌMỌ ỌDÚN KAN.

    GIFT FI EYÍN GÉ OKÓ OLÓLÙFẸ́ RẸ̀ BỌ́ SÍLẸ̀.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ILÉ IṢẸ́ OLÓGUN YAN ALUKORO OBÌNRIN ÀKỌ́KỌ́.

    ÀWỌN JÀǸDÙKÚ AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ANAMBRA.

    Àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú APC.

    ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢOJÚṢÒFIN MÉJÌ YAPA KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NNPP.

    Àmì ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíría

    ỌWỌ́ TẸ ONÍLÉ ÌTURA TÓ Ń PA ÀWỌN ARÌRÌNÀJÒ.

    ÀÀRẸ BOLA AHMED TINUBU KÉDE ÌPÍNLẸ̀ RIVERS NÍ ÌPÍNLẸ̀ PÀJÁWÌRÌ.

    KO PỌN DANDAN FÚN MI LÁTI PADÀ SÍPÒ GÓMÌNÀ – SIMINALAYI FUBARA.

    • Ìròyìn Agbègbè
    • Ọ̀rọ̀ Ààbò
    • Ọrọ̀-Ajé
    • Òṣèlú
  • Ìròyìn Tó Gbòde
  • Eré ìdárayá
  • Ìdánilárayá
    • All
    • Fiimu ati Nollywood
    • Orin
    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    LÁÀRIN TINUBU, EEDRIS ABDULKAREEM ÀTI WOLE SOYINKA.

    LÁÀRIN TINUBU, EEDRIS ABDULKAREEM ÀTI WOLE SOYINKA.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    MO TA ILÉ ÀTI Ọ̀NÀ MI LÓRÍ ÀÌSÀN ÌTỌ̀ ṢÚGÀ – AGBÓHÙNSÁFẸ́FẸ́.

    MO TA ILÉ ÀTI Ọ̀NÀ MI LÓRÍ ÀÌSÀN ÌTỌ̀ ṢÚGÀ – AGBÓHÙNSÁFẸ́FẸ́.

    TUFACE RA ÀWỌN AṢỌ TITUN FÚN ÌFẸ́ RẸ̀ TITUN; NATASHA

    TUFACE RA ÀWỌN AṢỌ TITUN FÚN ÌFẸ́ RẸ̀ TITUN; NATASHA

    ỌKÙNRIN MỌ́KÀNLÉLÓGÚN LÓ BÁ ÌYÀWÓ MI LÒ PỌ̀- ÌJỌBA LANDE

    MI Ò NÍ LE BÁ BABA TEE ṢIṢẸ́ PỌ̀ – ÌJỌBA LANDE.

    ÈMI NI ÌYÀWÓ ẸLẸ́Ẹ̀KEJE ỌKỌ MI :

    ÈMI NI ÌYÀWÓ ẸLẸ́Ẹ̀KEJE ỌKỌ MI :

    Ramadan Kareem!

    Ramadan Kareem!

    Àkàgbádùn

    Àkàgbádùn

    • Fiimu ati Nollywood
    • Orin
  • Ìgbé-Ayé
    • All
    • Ìlera
    • Ìrìn Àjò
    • Oge Ṣiṣe
    ÌJÀMBÁ INÁ LỌ́TÙN-ÚN LÓSÌ.

    ỌKỌ DÁNÁ SUN ÌYÀWÓ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ MẸ́TA NÍ ABIA.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒKÙNKÙN ṢEKÚ PA BENJAMIN NÍ IKORODU.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÌYÀWÓ NI OLAMIDE FẸ́ FỌ́ IRIN MỌ́ LÓRÍ TÓ FI BA ỌMỌ RẸ̀, ỌMỌ ỌDÚN KAN.

    GIFT FI EYÍN GÉ OKÓ OLÓLÙFẸ́ RẸ̀ BỌ́ SÍLẸ̀.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ILÉ IṢẸ́ OLÓGUN YAN ALUKORO OBÌNRIN ÀKỌ́KỌ́.

    ÀWỌN JÀǸDÙKÚ AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ANAMBRA.

    ONÍRÒYÌN KAN DÁKẸ́ NÍBI TÓ TI Ń MÚRA ÀTI KA ÌRÒYÌN.

    ONÍRÒYÌN KAN DÁKẸ́ NÍBI TÓ TI Ń MÚRA ÀTI KA ÌRÒYÌN.

    ÀÀRẸ BOLA AHMED TINUBU KÉDE ÌPÍNLẸ̀ RIVERS NÍ ÌPÍNLẸ̀ PÀJÁWÌRÌ.

    KO PỌN DANDAN FÚN MI LÁTI PADÀ SÍPÒ GÓMÌNÀ – SIMINALAYI FUBARA.

    ÀWỌN ẸLẸ́RÌÍ MẸ́TA LÓ JẸ́RÌÍ TAKO TIMILEHIN AJAYI NÍLÉ ẸJỌ́.

    ILÉ ẸJỌ́ YỌ̀ǸDA ÌYÓKÙ HAFSOH FÚN ÀWỌN ÒBÍ RẸ̀.

    ARÁBÌNRIN FIJABI KÉ SÍ ILÉ ÌWÉ GÍGA BABCOCK LÁTI WÁ ỌMỌ RẸ̀ SÍTA.

    A Ó FI ÒFIN GBÉ OLADIPUPO – ILÉ ÌWÉ GÍGA BABCOCK.

    Trending Tags

    • Golden Globes
    • Mr. Robot
    • MotoGP 2017
    • Climate Change
    • Flat Earth
    • Oge Sise
    • Ìlera
    • Ìrìn Àjò
  • Fọ́nrán
  • Àṣà Yorùbá
    • All
    • Àjọ̀dún Yorùbá
    • Ìtàn Yorùbá
    • Oríkì
    ÌYÀWÓ NI OLAMIDE FẸ́ FỌ́ IRIN MỌ́ LÓRÍ TÓ FI BA ỌMỌ RẸ̀, ỌMỌ ỌDÚN KAN.

    ILÉ ẸJỌ́ DÁJỌ́ IKÚ FÚN ỌKÙNRIN TÓ ṢEKÚ PA COMFORT JAMES.

    Àwọn agbébọn

    ÀWỌN AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÌPÍNLẸ̀ KWARA.

    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    ILÉ ỌBA Ọ̀YỌ́ KÒ JÓ ÀMỌ́ A Ó BU ẸWÀ SÍI – ỌBA OWOADE.

    ALÁÀFIN YAN OSUNTOLA NÍ OLÙBÁDÁMỌ̀RÀN PÀTÀKÌ.

    ILÉ ỌBA Ọ̀YỌ́ KÒ JÓ ÀMỌ́ A Ó BU ẸWÀ SÍI – ỌBA OWOADE.

    ILÉ ỌBA Ọ̀YỌ́ KÒ JÓ ÀMỌ́ A Ó BU ẸWÀ SÍI – ỌBA OWOADE.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    Àkàgbádùn

    Àkàgbádùn

    Ewì

    Ewì.

    • Àjọ̀dún Yorùbá
    • Ìtàn Yorùbá
    • Oríkì
  • Ààyè Olóòtú
  • Ilé Wa
  • Ìròyìn
    • All
    • ijamba oko
    • Ìròyìn Agbègbè
    • Ọ̀rọ̀ Ààbò
    • Ọ̀rọ̀ ìdílé
    • Ọrọ̀-Ajé
    • Òṣèlú
    ÌJÀMBÁ INÁ LỌ́TÙN-ÚN LÓSÌ.

    ỌKỌ DÁNÁ SUN ÌYÀWÓ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ MẸ́TA NÍ ABIA.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒKÙNKÙN ṢEKÚ PA BENJAMIN NÍ IKORODU.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÌYÀWÓ NI OLAMIDE FẸ́ FỌ́ IRIN MỌ́ LÓRÍ TÓ FI BA ỌMỌ RẸ̀, ỌMỌ ỌDÚN KAN.

    GIFT FI EYÍN GÉ OKÓ OLÓLÙFẸ́ RẸ̀ BỌ́ SÍLẸ̀.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ILÉ IṢẸ́ OLÓGUN YAN ALUKORO OBÌNRIN ÀKỌ́KỌ́.

    ÀWỌN JÀǸDÙKÚ AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ANAMBRA.

    Àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú APC.

    ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢOJÚṢÒFIN MÉJÌ YAPA KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NNPP.

    Àmì ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíría

    ỌWỌ́ TẸ ONÍLÉ ÌTURA TÓ Ń PA ÀWỌN ARÌRÌNÀJÒ.

    ÀÀRẸ BOLA AHMED TINUBU KÉDE ÌPÍNLẸ̀ RIVERS NÍ ÌPÍNLẸ̀ PÀJÁWÌRÌ.

    KO PỌN DANDAN FÚN MI LÁTI PADÀ SÍPÒ GÓMÌNÀ – SIMINALAYI FUBARA.

    • Ìròyìn Agbègbè
    • Ọ̀rọ̀ Ààbò
    • Ọrọ̀-Ajé
    • Òṣèlú
  • Ìròyìn Tó Gbòde
  • Eré ìdárayá
  • Ìdánilárayá
    • All
    • Fiimu ati Nollywood
    • Orin
    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    LÁÀRIN TINUBU, EEDRIS ABDULKAREEM ÀTI WOLE SOYINKA.

    LÁÀRIN TINUBU, EEDRIS ABDULKAREEM ÀTI WOLE SOYINKA.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    MO TA ILÉ ÀTI Ọ̀NÀ MI LÓRÍ ÀÌSÀN ÌTỌ̀ ṢÚGÀ – AGBÓHÙNSÁFẸ́FẸ́.

    MO TA ILÉ ÀTI Ọ̀NÀ MI LÓRÍ ÀÌSÀN ÌTỌ̀ ṢÚGÀ – AGBÓHÙNSÁFẸ́FẸ́.

    TUFACE RA ÀWỌN AṢỌ TITUN FÚN ÌFẸ́ RẸ̀ TITUN; NATASHA

    TUFACE RA ÀWỌN AṢỌ TITUN FÚN ÌFẸ́ RẸ̀ TITUN; NATASHA

    ỌKÙNRIN MỌ́KÀNLÉLÓGÚN LÓ BÁ ÌYÀWÓ MI LÒ PỌ̀- ÌJỌBA LANDE

    MI Ò NÍ LE BÁ BABA TEE ṢIṢẸ́ PỌ̀ – ÌJỌBA LANDE.

    ÈMI NI ÌYÀWÓ ẸLẸ́Ẹ̀KEJE ỌKỌ MI :

    ÈMI NI ÌYÀWÓ ẸLẸ́Ẹ̀KEJE ỌKỌ MI :

    Ramadan Kareem!

    Ramadan Kareem!

    Àkàgbádùn

    Àkàgbádùn

    • Fiimu ati Nollywood
    • Orin
  • Ìgbé-Ayé
    • All
    • Ìlera
    • Ìrìn Àjò
    • Oge Ṣiṣe
    ÌJÀMBÁ INÁ LỌ́TÙN-ÚN LÓSÌ.

    ỌKỌ DÁNÁ SUN ÌYÀWÓ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ MẸ́TA NÍ ABIA.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒKÙNKÙN ṢEKÚ PA BENJAMIN NÍ IKORODU.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    ÌYÀWÓ NI OLAMIDE FẸ́ FỌ́ IRIN MỌ́ LÓRÍ TÓ FI BA ỌMỌ RẸ̀, ỌMỌ ỌDÚN KAN.

    GIFT FI EYÍN GÉ OKÓ OLÓLÙFẸ́ RẸ̀ BỌ́ SÍLẸ̀.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ỌWỌ́ TẸ ÀWỌN MÁRÙN-ÚN TÍ WỌ́N TA ỌMỌ ỌWỌ́.

    ILÉ IṢẸ́ OLÓGUN YAN ALUKORO OBÌNRIN ÀKỌ́KỌ́.

    ÀWỌN JÀǸDÙKÚ AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ANAMBRA.

    ONÍRÒYÌN KAN DÁKẸ́ NÍBI TÓ TI Ń MÚRA ÀTI KA ÌRÒYÌN.

    ONÍRÒYÌN KAN DÁKẸ́ NÍBI TÓ TI Ń MÚRA ÀTI KA ÌRÒYÌN.

    ÀÀRẸ BOLA AHMED TINUBU KÉDE ÌPÍNLẸ̀ RIVERS NÍ ÌPÍNLẸ̀ PÀJÁWÌRÌ.

    KO PỌN DANDAN FÚN MI LÁTI PADÀ SÍPÒ GÓMÌNÀ – SIMINALAYI FUBARA.

    ÀWỌN ẸLẸ́RÌÍ MẸ́TA LÓ JẸ́RÌÍ TAKO TIMILEHIN AJAYI NÍLÉ ẸJỌ́.

    ILÉ ẸJỌ́ YỌ̀ǸDA ÌYÓKÙ HAFSOH FÚN ÀWỌN ÒBÍ RẸ̀.

    ARÁBÌNRIN FIJABI KÉ SÍ ILÉ ÌWÉ GÍGA BABCOCK LÁTI WÁ ỌMỌ RẸ̀ SÍTA.

    A Ó FI ÒFIN GBÉ OLADIPUPO – ILÉ ÌWÉ GÍGA BABCOCK.

    Trending Tags

    • Golden Globes
    • Mr. Robot
    • MotoGP 2017
    • Climate Change
    • Flat Earth
    • Oge Sise
    • Ìlera
    • Ìrìn Àjò
  • Fọ́nrán
  • Àṣà Yorùbá
    • All
    • Àjọ̀dún Yorùbá
    • Ìtàn Yorùbá
    • Oríkì
    ÌYÀWÓ NI OLAMIDE FẸ́ FỌ́ IRIN MỌ́ LÓRÍ TÓ FI BA ỌMỌ RẸ̀, ỌMỌ ỌDÚN KAN.

    ILÉ ẸJỌ́ DÁJỌ́ IKÚ FÚN ỌKÙNRIN TÓ ṢEKÚ PA COMFORT JAMES.

    Àwọn agbébọn

    ÀWỌN AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÌPÍNLẸ̀ KWARA.

    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    ÌGBÉYÀWÓ PRISCILLA MÌLÚ TÌTÌ.

    ILÉ ỌBA Ọ̀YỌ́ KÒ JÓ ÀMỌ́ A Ó BU ẸWÀ SÍI – ỌBA OWOADE.

    ALÁÀFIN YAN OSUNTOLA NÍ OLÙBÁDÁMỌ̀RÀN PÀTÀKÌ.

    ILÉ ỌBA Ọ̀YỌ́ KÒ JÓ ÀMỌ́ A Ó BU ẸWÀ SÍI – ỌBA OWOADE.

    ILÉ ỌBA Ọ̀YỌ́ KÒ JÓ ÀMỌ́ A Ó BU ẸWÀ SÍI – ỌBA OWOADE.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    Ìròyìn Jákèjádò.

    Àkàgbádùn

    Àkàgbádùn

    Ewì

    Ewì.

    • Àjọ̀dún Yorùbá
    • Ìtàn Yorùbá
    • Oríkì
  • Ààyè Olóòtú
No Result
View All Result
ÌWÉ ÌRÒYÌN YORÙBÁ
No Result
View All Result
Home Ààyè Olóòtú

ỌKỌ DÁNÁ SUN ÌYÀWÓ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ MẸ́TA NÍ ABIA.

Ìpalára tí owú jíjẹ le fà.

by Adeola Olanrewaju
May 20, 2025
in Ààyè Olóòtú, Ìgbé-Ayé, Ìròyìn, Ọ̀rọ̀ ìdílé
0
ÌJÀMBÁ INÁ LỌ́TÙN-ÚN LÓSÌ.
0
SHARES
1
VIEWS
Pín Lórí FacebookPín Lórí ThreadsPín Lórí TwitterPín Lórí Bluesky

Arákùnrin kan tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Udochi Amala ti dáná sun ìyàwó àti ọmọ rẹ̀ nítorí pé ó fura pé ìyàwó òun ń yan àlè.
Ẹni ogójì ọdún ni Udochi, agbègbè Onicha Ngwa ní ìjọba ìbílẹ̀ Obingwa ni wọ́n ń gbé. Òru ní nǹkan bíi aago méjì ní ọjọ́ Àbámẹ́ta ni Udochi da epo lé ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́tẹ́ẹ̀ta lórí tó sì ṣáná sí i.
Iná ran Udochi fúnra rẹ̀ náà àmọ́ ó ríbi sá jáde nígbà tí ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ jóná. Àlàyé tó ṣe náà ni pé òun ní ìjà pẹ̀lú ìyàwó òun lórí pé ó ń yan àlè àmọ́ òun kò mọ̀ pé ìjà náà le le tó báyìí. Udochi ní òun kò ká ọkùnrin mọ́ Amarachi ìyàwó rẹ̀ lórí àmọ́ òun mọ̀ pé ó ń yan àlè.
Alukoro fún ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Abia; Maureen Chinaka fi ìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀ fún àwọn akọ̀ròyìn, ó wí pé ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà kú lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ nígbà tí ìyàwó àti àwọn ọmọ méjì yóòkù padà kú sí ilé ìwòsàn lọ́jọ́ kejì. Àwọn ọlọ́pàá wí pé ìwádìí ń tẹ̀síwájú lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.
Kò sí ohun tó máa ń fa irú nǹkan báyìí ju owú jíjẹ lọ, ìjàm̀bá tí owú jíjẹ ti ṣe láàrín lọ́kọláya àti àwọn olólùfẹ́ kìí ṣe kékeré. Ó le débi pé obìnrin mìíràn yóò gé nǹkan ọmọkùnrin ọkọ rẹ̀ ni féú.
Oríṣìí ìròyìn nípa èyí ni a ti kọ sẹ́yìn. Èyí tó ṣẹlẹ̀ ní ìpínlẹ̀ Rivers lẹ́nu lọ́ọ́lọ́ yìí gan-an kò tíì tutù. Ohun tí a gbọ́ ni pé Gift; ẹni ọdún mẹ́tàlélógójì fi eyín gé okó Sunday; olólùfẹ́ rẹ̀ bọ́ sílẹ̀.
Sunday tó má wá ń kí i ló tún dé pé òun fẹ́ ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú rẹ̀, Gift kọ̀ jálẹ̀ pé òun kò ṣe nítorí pé Sunday ti mu àwọn èròjà agbára ní èyí tí kò ní jẹ́ kó tètè ṣe tán.
Ìròyìn wí pé Sunday kò gbà, ó fi agídí bo Gift mọ́lẹ̀ ni Gift bá gbé okó rẹ̀ sẹ́nu ó sì fi eyín já ìdajì rẹ̀ bọ́ sílẹ̀.
Ariwo Sunday ni àwọn ará ilé fi bò wọ́n, wọ́n tilẹ̀ fẹ́ lu Gift pa ni àwọn ọlọ́pàá ló gbà á sílẹ̀.
Àwọn ọlọ́pàá ti gbé Sunday lọ sí ilé ìwòsàn fún ìtọ́jú wọ́n sì ti mú Gift sí àhámọ́. Ó ku àlàyé tí Sunday yóò ṣe fún ìyàwó ilé rẹ̀ báyìí.
Ní ìpínlẹ̀ èkìtì lóṣù tó kọjá, Joy rí ẹ̀wọ̀n he nígbà tó fi abẹ fa ẹpọ̀n Ibrahim tó jẹ́ olólùfẹ́ rẹ̀ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Ìròyìn náà kà báyìí pé:
Ilé ẹjọ́ tó fìkàlẹ̀ sí ìpínlẹ̀ Ekiti ti pàṣẹ kí Joy Ikoja ó lọ rọ́kún lọ́gbà ẹ̀wọ̀n lórí ẹ̀sùn pé ó fa ẹpọ̀n ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
Ẹni ọgún ọdún ni Joy Ikoja, a kò tíì le sọ pàtó ohun tó ṣẹlẹ̀ láàrin òun àti ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀; Ibrahim Usman tó fi fi abẹ fa ẹpọ̀n rẹ̀ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
Ọjọ́ ìṣẹ́gun ni Joy fi ojú ba ilé ẹjọ́, ẹjọ́ náà kò le parí lọ́jọ́ náà fún àwọn ìdí tó pọ̀ ni adájọ́ bá pàṣẹ kí wọn ó fi Joy sí ọgbà ẹ̀wọ̀n kan ní Ado-Ekiti títí di ọjọ́ kejìlélógún, oṣùn Igbe tó lọ yìí.
Agbẹjọ́rò rẹ̀ gbìyànjú láti rọ ilé ẹjọ́ pé kí wọn ó gba onídùúró rẹ̀ kí ó le máa gba ilé wá jẹ́jọ́, ó wí pé afurasí náà kò mọ nǹkankan nípa ẹ̀sùn náà.
Adájọ́ Olatomiwa Daramola fagi lé ẹ̀bẹ̀ agbẹjọ́rò Joy ó sì pàṣẹ kí wọn ó mú un lọ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n Ado-Ekiti títí di ọjọ́ ìgbẹ́jọ́ tó ń bọ̀.
Kò tán síbẹ̀ o, ní ìpínlẹ̀ Ekiti yìí kan náà ni ìyàwó ilé ti fi àdá gé okó ọkọ rẹ̀ féú tí ọkọ náà sì ṣáa ládàá pa. ìròyìn náà kà báyìí pé:
Tọkọtaya kan tí wọ́n ń gbé ní Ita-Eku ní igirigiri, Ado Ekiti tíí ṣe olú ìlú ìpínlẹ̀ Ekiti ni wọ́n ṣá ara wọn ládàá pa ní òru mọ́jú.
Ọ̀rọ̀ náà ṣe àwọn ọmọ wọn gan-an ní kàyéfì, kò sí ẹni tó le sọ pàtó bí ó ṣe ṣẹ̀lẹ̀ nítorí wọ́n ti ìlẹ̀kùn mọ́rí.
Àkọ́bí wọn lọ́kùnrin, ọmọ ọdún mẹ́tàlá ṣe àlàyé bí ọ̀rọ̀ náà ṣe ṣẹlẹ̀ lálẹ́ ọjọ́ náà pé bàbá àwọn dé ní nǹkan bíi aago mẹ́sàn-án alẹ́, ó ní òun kò le jẹun àyàfi bí ìyá àwọn bá dé.
Nígbà tí ìyá wọn dé, gbogbo wọn jọ jẹun, wọ́n gbàdúrà, bàbá wọn ka bíbélì sí wọn létí, gbogbo wọn sì wọ yàrá wọn lọ sùn.
Nígbà tó di òru ni àwọn ọmọ bẹ̀rẹ̀ sí ní gbọ́ ìró àdá láti inú yàrá bàbá wọn, títì láti inú ni ìlẹ̀kùn wọn wà, àwọn ọmọ bá lọ pe awon ará àdúgbò, nígbà tí wọn yóò fi dé, wẹ́lo ni yàrá náà kò sí ariwo kankan mọ́.
Àwọn ọ̀dọ́ àdúgbò já ìlẹ̀kùn yàrá náà, òkú tọkọtaya ni wọ́n bá nínú àgbàrá ẹ̀jẹ̀ pẹ̀lú àwọn àpá àdá tó jinú lára wọn. Kódà, nǹkan ọmọkùnrin bàbá ti dá dúrò nílẹ̀; kò sí lábẹ́ rẹ̀ mọ́.
Ohun tí wọ́n le sọ nípa ipò tí wọ́n bá wọn náà ni pé bóyá ìyàwó gé okó ọkọ rẹ̀ ni ọkọ náà bá kó àdá bò ó ni wọ́n bá ṣá ara wọn pa. Èrò lásán ni èyí, kò ṣojú ẹnìkankan.
Àwọn akọ̀ròyìn bi ọmọ náà léèrè pé ṣé àwọn òbí wọn máa ń jà tẹ́lẹ̀.
Ọmọ yìí fèsì pé ìjà kìí ṣe ohun titun nílé àwọn nítorí pé gbogbo ìgbà ni ìyá àwọn máa ń bá bàbá àwọn jà lórí ẹ̀sùn pé bàbá àwọn ń yan àlè.
Ó wí pé bàbá àwọn máa ń bá àwọn ṣeré dáadáa àmọ́ tí ìyá awo bá ti dé ni àyà rẹ̀ ó máa já. Ọmọ yìí wí pé bàbá òun sọ fún òun lọ́jọ́ kan pé ẹ̀rù ìyá òun ń ba òun.
Àmọ́ ní alẹ́ ọjọ́ tí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ṣẹ̀, ìjà ni àwọn ń retí bí ìyá àwọn ṣe dé àmọ́ ẹ̀rín àti ọ̀yàyà ni ìyá wọn bá wọlé, inú gbogbo wọn dùn láìmọ̀ pé gbẹgẹdẹ ó padà gbiná lóru.
Ọmọ mẹ́rin ló wà láàárín tọkọtaya yìí, ọmọ ọdún mẹ́tàlá ni àkọ́bí wọn, kò sí èyí tó tójú bọ́ nínú wọn.
Àwọn ará àdúgbò náà kín àlàyé tí ọmọ yìí ṣe lẹ́yìn. Wọ́n ní fádèyí olóró àdúgbò ni arábìnrin náà, gbogbo ìgbà ni ó máa ń bá ọkọ rẹ̀ jà, á wí pé ọkọ òun ń yan àlè.
Wọ́n ní ohun tó ṣẹlẹ̀ lóru ọjọ́ náà gan-an kò yé ẹnikẹ́ni tààrà nítorí pé wọ́n ti ilẹ̀kùn mọ́rí. Àwọn ará àdúgbò tilẹ̀ ṣe aájò wọn dé ilé ìwòsàn àmọ́ ẹ̀pa kò bá oró mọ́.
Ọ̀rọ̀ yìí kan ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá gbọ̀ngbọ̀n nítorí pé ọlọ́pàá ni ọkùnrin náà kó tó kú. Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá wí pé àwọn ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Irú ìròyìn báyìí kìí ṣe ohun tó dára tó láwùjọ, bí òpin yóò ṣe dé bá irú ìṣẹ̀lẹ̀ báyìí di ọwọ́ gbogbo wa.

Facebook Comments Box
Tags: #iweiroyinyoruba#ìwéròyìnyorùbá #NewsOnline#newsfeedAfojúsùn Iwe Iroyin Yorubanews onlinenewsonlinetrending
Adeola Olanrewaju

Adeola Olanrewaju

Discussion about this post

Recommended

ỌKỌ̀ TẸ ÀWỌN ÈÈYÀN PA LỌ́JỌ́ ỌDÚN ÀJÍǸDE.

ỌKỌ̀ TẸ ÀWỌN ÈÈYÀN PA LỌ́JỌ́ ỌDÚN ÀJÍǸDE.

4 weeks ago
Àkàgbádùn

Àkàgbádùn

3 months ago

Popular News

  • ÌJÀMBÁ INÁ LỌ́TÙN-ÚN LÓSÌ.

    ỌKỌ DÁNÁ SUN ÌYÀWÓ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ MẸ́TA NÍ ABIA.

    0 shares
    Share 0 Tweet 0
  • ÀWỌN OLÓGUN TI ṢEKÚ PA ỌLỌ́WỌ́ Ọ̀TÚN BELLO TURJI NÍ SOKOTO.

    0 shares
    Share 0 Tweet 0
  • ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒKÙNKÙN ṢEKÚ PA BENJAMIN NÍ IKORODU.

    0 shares
    Share 0 Tweet 0
  • GIFT FI EYÍN GÉ OKÓ OLÓLÙFẸ́ RẸ̀ BỌ́ SÍLẸ̀.

    0 shares
    Share 0 Tweet 0
  • ÀWỌN JÀǸDÙKÚ AGBÉBỌN ṢE ÌKỌLÙ SÍ ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ANAMBRA.

    0 shares
    Share 0 Tweet 0

Connect with us

Newsletter

Lorem ipsum dolor sit amet, consectetuer adipiscing elit. Aenean commodo ligula eget dolor.
SUBSCRIBE

Category

Site Links

  • Register
  • Log in
  • Entries feed
  • Comments feed
  • WordPress.org

About Us

We bring you the best Premium WordPress Themes that perfect for news, magazine, personal blog, etc. Check our landing page for details.

  • About
  • Advertise
  • Careers
  • Contact

© 2024 The Morganable Media Group - Ìwé Ìròyìn Yorùbá is owned by The Morganable Media Group

Welcome Back!

Sign In with Facebook
Sign In with Google
Sign In with Linked In
OR

Login to your account below

Forgotten Password? Sign Up

Create New Account!

Sign Up with Facebook
Sign Up with Google
Sign Up with Linked In
OR

Fill the forms below to register

All fields are required. Log In

Retrieve your password

Please enter your username or email address to reset your password.

Log In
No Result
View All Result
  • Ilé Wa
  • Ìròyìn
    • Ìròyìn Agbègbè
    • Ọ̀rọ̀ Ààbò
    • Ọrọ̀-Ajé
    • Òṣèlú
  • Ìròyìn Tó Gbòde
  • Eré ìdárayá
  • Ìdánilárayá
    • Fiimu ati Nollywood
    • Orin
  • Ìgbé-Ayé
    • Oge Sise
    • Ìlera
    • Ìrìn Àjò
  • Fọ́nrán
  • Àṣà Yorùbá
    • Àjọ̀dún Yorùbá
    • Ìtàn Yorùbá
    • Oríkì
  • Ààyè Olóòtú

© 2024 The Morganable Media Group - Ìwé Ìròyìn Yorùbá is owned by The Morganable Media Group