Ilé ẹjọ́ gíga ìjọba tó fìkàlẹ̀ sí Kaduna ti pàṣẹ kí Gómìnà ìpínlẹ̀ Kaduna tẹ́lẹ̀rí; Nasir El-Rufai àti àwọn márùn-ún mìíràn pé kí wọn ó san ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún mílíọ́nù náírà #900M owó ìtanràn fún títẹ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn lójú mọ́lẹ̀ ní ọdún 2019.
Wọ́n ní El-Rifai ti àwọn àgbààgbà ìlú Adara mọ́lé ní ọdún 2019 lọ́nà tí kò bá òfin mu ní èyí tó tẹ ẹ̀tọ́ wọn lójú mọ́lẹ̀.
Adájọ́ Hauwa’u Buhari ló gbé ìdájọ́ náà kalẹ̀ ní èsì sí ẹjọ́ tí àwọn àgbààgbà náà pè tako El-Rufai. Lẹ́yìn náà ló pàṣẹ kí wọn ó san mílíọ́nù mẹ́wàá náírà owó àtúnṣe gbogbogbò àti mílíọ́nù mẹ́wàá náírà owó àtúnṣe pàtàkì fún ọ̀gá ọlọ́pàá pátápátá àti kọmíṣọ́nà ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Kaduna.
Agbẹjọrò ìjọba lórí ẹjọ́ yìí wí pé ìdájọ́ yìí fi hàn pé òfin orílẹ̀-èdè wa le mú ẹnikẹ́ni tó bá rú òfin.
Àlàyé ẹ̀sùn náà lọ báyìí pé lẹ́yìn tí El-Rufai fi ipò Gómìnà sílẹ̀ tán ni wọ́n pe ẹjọ́ náà takò ó pé ó tẹ ẹ̀tọ́ àwọn èèyàn náà lójú mọ́lẹ̀.
Wọ́n ní El-Rufai pàṣẹ kí àwọn ọlọ́pàá ó ti àwọn àgbààgbà ìlú Adara mọ́lé lórí bí àwọn kan ṣe ikú pa olórí ìlú Adara ìgbà náà; Dọ́kítà Raphael Maiwada Galadima. Kọmíṣọ́nà ọlọ́pàá kan wà lára àwọn tó pàṣẹ kí wọn ó tì mọ́lé nígbà náà.
Ọ̀gá ọlọ́pàá pátápátá ìgbà náà ló dá àwọn èèyàn náà sílẹ̀ nígbà tí kò rí ẹ̀rí pé àwọn ló ṣekú pa olórí ìlú náà. Kò sí awuyewuye lórí ọ̀rọ̀ náà láti ìgbà náà mọ́ títí di àsìkò yìí tí wọ́n pe ẹjọ́ náà tako El-Rufai pé ó tẹ ẹ̀tọ́ àwọn ẹni náà lójú mọ́lẹ̀.
Ìbéèrè tí ọ̀pọ̀ àwọn èèyàn ń bèèrè lásìkò yìí ni pé ṣé kìí ṣe pé ejò lọ́wọ́ nínú lórí ọ̀rọ̀ yìí, ṣé nítorí pé El-Rufai kọ̀ láti ṣe àtìlẹyìn fún ààrẹ Bola Ahmed Tinubu lórí ètò ìdìbò ọdún 2027 ni wọ́n ṣe ṣètò ẹ̀sùn àti ìdájọ́ yìí tako ó?
Ẹnìkan tilẹ̀ sọ pé bí El-Rufai bá fi le ta kọ́sọ́ sínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC padà báyìí ni wọn yóò wọgí lé ẹjọ́ àti ìdájọ́ yìí.
Àwa kò le sọ bí òótọ́ ni èyí bí òótọ́ kọ́, ohun tí a le sọ ni pé gbogbo wa la mọ̀ pé El-Rufai ti yapa kúrò nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC tí òun àti ẹgbẹ́ náà sì jọ lérí sí ara wọn.
Ìròyìn náà kà báyìí pé:
Ẹgbẹ́ òṣèlú APC ti sọ̀rọ̀ lórí yíyapa tí El-Rufai yapa kúrò nínú ẹgbẹ́ òṣèlú náà lọ sínú ẹgbẹ́ òṣèlú SDP. Wọ́n wí pé kò tu irun kan lára wọn, wọ́n láwọn kò tilẹ̀ mọ̀ pé èèyàn kúrò rárá.
Wọ́n wí pé kò sọ́rọ̀ nínú ohun tó sọ pé òun yóò kó àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú jọ láti dìbò tako ìyànsípò Bola Ahmed Tinubu nínú ìdìbò ọdún 2027, wọ́n lọ́rọ̀ rírùn ni.
Ẹgbẹ́ òṣèlú APC wí pé kò sí àwọn èèyàn tí El-Rufai le kó jọ tó le pa ìdìbò ọdún 2027 lára nítorí pé Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu náà ni yóò wọlé.
Wọn kò ṣàì má mẹ́nuba pé àmọ́ lọ̀rò El-Rufai kò mọ́ ara ẹran àti pé ìtì ọ̀gẹ̀dẹ̀ lọ̀rọ̀ rẹ̀, kò tó ohun tí àwọn ó máa wá yọ àdá sí.
Ọ̀rọ̀ yìí wá dà bí orin tí wọ́n máa ń kọ pé bí yó lọ kó lọ, ìgbà tí ò lọ kí ló ṣe?
Nasir El-Rufai, ẹni tó ti fìgbà kan jẹ́ Gómìnà ìpínlẹ̀ Kaduna tó sì tún jẹ́ èèkan nínú ẹgbẹ́ náà kọ̀wé ìyapa ṣọwọ́ sí ẹgbẹ́ náà pé òun kò bá wọn ṣe mọ́, ó tó gé, àlubàtá kò tún gbọdọ̀ máa dárin. El-Rufai wí pé òun ti dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú SDP níbi tí òun yóò ti ní àǹfààní àti gòkè àgbà.
Ẹ̀sùn tó fi kan ẹgbẹ́ òṣèlú APC ni pé wọn kọ iyán òun kéré, wọn ò tún fewé bò ó, ó wí pé òun wà lára àwọn tó pilẹ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú APC pẹ̀lú èrò pé yóò gbe òun dalẹ́ láìmọ̀ pé ṣe ni wọn yóò já òun kulẹ̀. Ó ní àwọn adarí ẹgbẹ́ náà kò ka àmọ̀ràn òun kún rárá, gbogbo ọ̀rọ̀ òun kò tà létí wọn, ẹ̀yin náà sì mọ̀ pé ìlú tí wọn kò bá ti fẹ́ni, a kìí dárin níbẹ̀. Ìdí rèé tí ó fi yapa lọ sínú ẹgbẹ́ òṣèlú SDP pẹ̀lú èrò pé yóò gbe òun.
El-Rufai ṣe ìlérí pé òun yóò kó àwọn èèyàn jọ láti dìbò tako ààrẹ Bola Ahmed Tinubu nínú ìdìbò ọdún 2027.
Ẹgbẹ́ òṣèlú APC ti wá fèsì báyìí pé ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò le mu àwọn lómi nítorí pé balùwẹ̀ rẹ̀ tó fẹ́ kún ju odò lọ, irọ́ lásán ni.
Kò tán síbẹ̀ o, lórí aáwọ̀ tó wà láàrín rẹ̀ àti ẹgbẹ́ òṣèlú APC yìí náà ni àwọn èèyàn ṣe bi í léèrè pé kín ni ó wá lọ sí ilé ààrẹ àná; Muhammadu Buhari tó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú APC. Wọ́n ní bí yóò bá jẹ́ ọ̀ṣáká kó jẹ́ ọ̀sáká, bí yóò bá sì jẹ́ òṣoko kó jẹ́ òṣoko, kín ni ó ń wá nílé ẹni tó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú tó kọ̀ sílẹ̀.
Nasir El-Rufai fèsì o, ó ní òun kò yí ìpinnu òun padà, òun ti kí ẹgbẹ́ òṣèlú APC pé ó dàáàrọ́ òun ò sì tún le padà kí ẹgbẹ́ náà káalẹ́ mọ́. Èsì rẹ̀ kà báyìí pé:
Oúnjẹ òsán lásán ni mo yà jẹ ní ilé ààrẹ àná; Muhammadu Buhari.
Ó ṣe àlàyé pé òun àti ikọ̀ òun ń bọ̀ láti mọ́ṣáláṣí tó wà ní òpópòná Yahaya níbi tí àwọn ti kí irun Jímọ̀, àwọn yà ní ilé Muhammadu Buhari láti ṣe é ní pẹ̀lẹ́ kí àwọn sì kí olùtọ́ni àwọn ìyẹn Muhammadu Buhari.
Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tẹ̀síwájú pé kí àwọn olólùfẹ́ òun ó má mikàn nítorí pé òun kò le padà sínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC, ó ní kí wọn ó máa bá òun lọ nínú ẹgbẹ́ òṣèlú SDP tí òun wà báyìí.
Ohun tó bí ọ̀rọ̀ yìí ni àbẹ̀wò tí El-Rufai àti àwọn àgbà olóṣèlú lọ ṣe sí Muhammadu Buhari lọ́jọ́ Ẹtì ní ilé rẹ̀ tó wà ní Kaduna. A rí igbákejì ààrẹ ìjẹrin; Atiku Abubakar tó ṣaájú àwọn èèyàn náà wọ inú ilé Buhari. Lára àwọn tí wọ́n jọ kọ́wọ̀ọ́ lọ ni Gómìnà ìpínlẹ̀ Kaduna tẹ́lẹ̀rí; Nasir El-Rufai, Gómìnà ìpínlẹ̀ Sokoto tẹ́lẹ̀rí; Aminu Tambuwal, Mínísítà fún àtẹ̀jạde tẹ́lẹ̀rí; Isa Pantami, Gómìnà ìpínlẹ̀ Imo tẹ́lẹ̀rí; Achike Udenwa, Gómìnà ìpínlẹ̀ Benue tẹ́lẹ̀rí; Gabriel Suswam àti Gómìnà ìpínlẹ̀ Adamawa tẹ́lẹ̀rí; Jibirlla Bindow.
Gbogbo wọn ní wọ́n ti di ipò òṣèlú mú tẹ́lẹ̀rí tí wọ́n sì lọ ilé ààrẹ tẹ́lẹ̀rí, a kò mọ ohun tí wọ́n ti sọ tẹ́lẹ̀rí àmọ́ Gómìnà Kaduna tẹ́lẹ̀rí wí pé nǹkan kan kò tẹ́lẹ̀rí àbẹ̀wò náà.
Ní bạ́yìí tí ilé ẹjọ́ pàṣẹ pé kí ó san owó ìtanràn, àwọn èèyàn fẹ́ mọ̀ bóyá lórí òdodo ni àbí lórí òṣèlú, El-Rufai náà ló le sọ bó ṣe jẹ́.
Discussion about this post