Gbọ̀gán ìdánwò ilé ìwé girama ìjọba tó wà ní Namnai ní ìjọba ìbílẹ̀ Gassol ní ìpínlẹ̀ Taraba ti wó lé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó ń ṣe ìdánwò àṣekágbá ilé ìwé girama WAEC lórí lẹ́yìn àrọ̀ọ̀rọ̀dá òjó.
Kò sí ẹni tó gbé ẹ̀mí mì nínú ìṣẹ̀lẹ̀ yìí àmọ́ wọ́n fi ara pa yánnayàna, Kódà, àwọn kan dá lápa nígbá tí àwọn mìíràn dá lẹ́sẹ̀. Gbogbo àwọn akẹ́kọ̀ọ́, olùkọ́, agùnbánirọ̀ àti alámòójútó ti balẹ̀ sí ilé ìwòsàn lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà.
Alhaji DanAzumi Lauris; ẹni tó jẹ́ ará àdúgbò náà ṣe àlàyé pé gbọ̀gán náà dà wó ní nǹkan bíi aago mẹ́fà ìrọ̀lẹ́ nígbà tí àwọn ikọ̀ kejì ń ṣe ìdánwò lọ́wọ́. Àwọn ikọ̀ kìíní ti parí wọ́n sì ti lọ sí ilé wọn ṣáájú ìṣẹ̀lẹ̀ náà. Alhaji Lauris wí pé òjò náà fẹ́ atẹ́gùn tó le púpọ̀ ló mú kí gbọ̀gán náà ó dà wó.
Ó wí pé kìí ṣe gbọ̀gán ìdánwò náà nìkan ló dà wó, àwọn ilé kan náà ní àdúgbò náà fara gbá nínú àtẹ́gun òjò náà.
Òjò yìí kò bá má bá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà ní ilé ìwé àmọ́ àwọn adarí ìdánwò náà kò tètè dé, ó tó nǹkan bíi aago kan ọ̀sán kí wọ́n tó kó àwọn ìwé ìdánwò dé, èyí ló fà á tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà fi pẹ́ nílé ìwé lánàá.
Gbogbo akitiyan láti bá kọmíṣọ́nà fún ètò ẹ̀kọ́ ìpínlẹ̀ Taraba; Dọ́kítà Augustina Godwin sọ̀rọ̀ kò so èso rere lásìkò yìí.
Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó lọ ṣe ìdánwò WAEC yìí kan náà ni ọkọ̀ àjàgbé ti tẹ̀ pa báyìí.
A gbọ́ pé:
Akẹ́kọ̀ọ́ kan tó ń ṣe ìdánwò àṣekágbá oníwèé mẹ́wàá WAEC lọ́wọ́ ni ọkọ̀ àjàgbé kan ti tẹ̀ pa báyìí ní ìpínlẹ̀ Ogun. Ohun tí a gbọ́ ni pé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ìwé girama Seico tó wà ní Ikangba ní Ijebu-Ode ń bọ̀ láti ilé ìwé lẹ́yìn ìdánwò ọjọ́ Ẹtì, inú wọn ń dùn wọ́n sì mú ìwé ìbéèrè ìdánwò náà lọ́wọ́ nígbà tí ọkọ̀ àjàgbé eléjò kan pàdánù ìjánu rẹ̀ lórí eré tó sì wọ àárín wọn.
Akẹ́kọ̀ọ́bìnrin kan ló tẹ̀ pa lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ nígbà tí ó ṣe àwọn mìíràn léṣe. Ọ̀gbẹ́ni Eko Nicholas, ẹni tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣojú rẹ̀ ṣe àlàyé péo ọkọ̀ àjàgbé náà pàdánù ìjánu rẹ̀ ní òpópónà Molipa tó sì já wọ àárín àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà kó tó wá lọ fi orí sọ ọgbà ilé ìjọsìn ìràpadà tó wà ní ibẹ̀.
Nicholas wí pé òun kò le sọ pàtó òun tó mú kí ọkọ̀ náà ó pàdánú ìjánu rẹ̀, ó wí pé láti ìgbà tí ìjọba ti tún ọ̀nà náà ṣe tó sì ti já geere ni ìjàm̀bá ti ń wáyé lójú ọ̀nà náà látàrí eré àsápajúdé àwọn awakọ̀. Ó ní òun dá ìjọba lẹ́bi àwọn ìjàm̀bá náà nítorí pé wọn kò ṣe kankéré ìdánà tí yóò mú àdínkù bá eré àsápajúdé sí ọ̀nà náá.
Àlàyé Nicholas tẹ̀síwájú síi pé ó di èèyàn mẹ́fà tí ó ti bá ìjàm̀bá lọ lójú ọ̀nà náà láàrín oṣù Èrèlé tí wọ́n ṣe ọ̀nà náà sí àsìkò yìí. Ó wí pé ilé ìwé pọ̀ ní agbègbè náà ní èyí tó mú kí àwọn ọmọ ó pọ̀ ní ọ̀nà náà. Àwọn onílé agbègbè náà ti kọ ìwé sí ìjọba pé kí wọn ó wá ṣe kankéré ìdánà sí ojú ọ̀nà náà àmọ́ wọn kò tíì rí èsì kankan gbà títí di àsìkò yìí.
Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá náà sọ̀rọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà, wọ́n ní àwọn gba ìfisùn nípa ìjàm̀bá náà àti akẹ́kọ̀ọ́ tó gbẹ́mìí mì ìwádìí sì ti bẹ̀rẹ̀ lórí rẹ̀.
Ká mẹ́nuba ìṣẹ̀lẹ̀ ilé tó dà wó ní Ikorodu. Òkú mọ̀lẹ́bí kan náà mẹ́ta ni wọ́n ti rí báyìí.
Ìròyìn náà kà báyìí pé:
Àwọn òṣìṣẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ pàjáwìrí ti ṣe àwárí àwọn òkú mẹ́ta tí wọ́n jẹ́ mọ̀lẹ́bí kan lábẹ́ èérún ilé tó dà wó ní Ota-Ona, Ikorodu. Orúkọ àwọn mọ̀lẹ́bí náà ni Maleek; ọmọ ọdún mẹ́rìndínlógún, Ameerah; ọmọ ọdún mẹ́tàlá àti àbúrò bàbá wọn; Bolaji; ẹni ọdún mẹ́tàléláàdọ́rin.
Àlàyé tí a rí gbà ni pé ẹnìkan nínú mọ̀lẹ́bí náà tó wà lókè òkun ló ni ilé náà tí Bolaji sì ń báa mójútó o, lọ́jọ́ tí ilé yìí dà wó, Bolaji kó àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lẹ́yìn láti lọ ṣe àbẹ̀wò sí ilé náà kó tó di pé ó dà wó lé wọn lórí tí gbogbo wọn sì kú.
Àwọn èèyàn mẹ́wàá mìíràn tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ ni wọ́n rí yọ jáde láàyé àmọ́ àwọn mọ̀lẹ́bí tó ni ilé náà gan-an ló gbẹ́mìí mìn.
A mú ìròyìn bí ilé náà ṣe dà wó wá nígbà tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ṣẹlẹ̀ pé:
Ilé alájà méjì kan tí wọ́n ń kọ́ lọ́wọ́ ní agbègbè Ota-Ona ní Ikorodu ti dà wó lulẹ̀ lọ́sàn-án àná, ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n, oṣù Èbìbí.
Rasheed Fatuga ló kọ ọ́ sí ojú òpó ìbánidọ́rẹ̀ẹ́ rẹ̀ pé ilé náà tó wà ní àdojúkọ ilé epo Mobil ti dà wó lulẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọlọpọ̀ àwọn òṣìṣẹ́ nínú rẹ̀.
Kíá ni àwọn òṣìṣẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ pàjáwìrì ti dé ibẹ̀. Àwọn èèyàn márùn-ún ni wọ́n ti rí yọ láàyè báyìí àmọ́ a kò le sọ pàtó iye àwọn èèyàn tó ṣì wà lábẹ́ èérún ilé náà.
Ní báyìí, àwọn òṣìṣẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ pàjáwìrì ti ṣe àwárí òkú àwọn ọmọdé méjì àti àgbà kan tí wọ́n ni ilé náà wọ́n sì tún rí àwọn mẹ́wàá mìíràn yọ láàyè.
Lórí ohun tó ṣe òkùnfà dídàwó náà:
Àwọn tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣojú wọn di ẹ̀bi rẹ̀ ru àwọn òṣìṣẹ́ ibẹ̀. Wọ́n ní àwọn ló kọ ilé náà lóní yẹ̀bùyẹ́bù tó fi di pé ó dà wó lulẹ̀ báyìí.
Discussion about this post