Àwọn ọlọ́pàá ti mú àwọn afurasí mẹ́rìnlá tí wọ́n jẹ́ ikọ̀ One-chance ní Idimu, ìpínlẹ̀ Èkó. Àwọn afurasí yìí máa ń ṣiṣẹ́ káàkiri Èkó àmọ́ Idimu ni ibùdó wọn wà, ibẹ̀ ni wọ́n kọ́ ilé kótópó kan sí tí wọ́n ṣe bíi ilédì awo àmọ́ tó jẹ́ pé àwọn èèyàn ni wọ́n ń jígbé sí ibẹ̀.
Ọ̀pọ̀ àwọn èèyàn ló máa ń kọjá lára ilé yìí tí wọn kò sì fura nítorí wọ́n rò pé ilédì ni. Ọkọ̀ mẹ́fà ni àwọn ẹni yìí ń lò láti ṣe iṣẹ́ wọn.
Wọn yóò gbé àwọn èrò tó ń lọ sí ibi iṣẹ́ àti ibi ọjà wọn ní ìdájì àti ní alẹ́ tí wọ́n bá ń padà bọ̀. Ẹni tí wọ́n gbé tó bá rí owó san yóò gba ìtúsílẹ̀ nígbà tí ẹni tí kò bá rí owó san yóò wà ní ilé náà títí àwọn ẹbí rẹ̀ ó fi rí owó san.
Kọmíṣọ́nà ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Èkó; Olohundare Jimoh ló ṣaájú àwọn akọ̀ròyìn lọ sí ilé náà tó sì fi ojú àwọn afurasí náà hàn.
Ó ṣe àlàyé pé ní ìdájí ọjọ́ Àìkú ni àwọn ọlọ́pàá mú mẹ́ta nínú wọn nígbà tí wọ́n ń ṣe àyẹ̀wò àwọn ọkọ̀ tó ń kọjá, wọ́n dá ọkọ̀ wọn dúró wọ́n sì bá ẹni tí wọ́n gbé náà tí ìyà ti pá a lórí, wọ́n mú wọn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, àwọn ni wọ́n júwe àwọn ìyókù wọn àti bi tí wọ́n ti ń pàdé.
Demola Adelua ni olórí ikọ̀ yìí, ó ti lé ní ọdún mẹ́jọ tí ó ti ń ṣe é, yàtọ̀ sí ikọ̀ tí wọ́n mú yìí, ikọ̀ mẹ́fà mìíràn ni ó tún ń darí ní Èkó.
Ó ṣe àlàyé pé ìdájí kùtù hàì ni àwọn ọmọṣẹ́ rẹ̀ yóò ti gbé ọkọ̀ jáde, wọn yóò gbé àwọn tó ń jí lọ síbi iṣẹ́ ní ìgboro Èkó, ìdajì ọ̀nà ni wọn yóò ti gba gbogbo owó lọ́wọ́ rẹ̀ kí wọ́n tó já a sílẹ̀ tàbí gbé e lọ sí ibùdó bí kò bá rí owó san. Wọn yóò tún ṣe bẹ́ẹ̀ ní alẹ́ pátápátá fún àwọn tó bá pẹ́ níta.
Ìdí ni pé ọ̀nà máa ń dá ní àwọn àsìkò yìí àti pé àwọn ọlọ́pàá kìí dé òde lásìkò yìí àfi ọjọ́ tí wọ́n mú wọn náà. Ó tún ṣe àlàyé pé àwọn tí wọ́n máa ń jí lọ sí ṣọ́ọ̀ṣì lọ́jọ́ Àìkú àti àwọn tó máa ń ti ìṣọ́ òru bọ̀ ló máa ń ṣe àgbákò àwọn jù.
Ọkọ̀ Sienna ni ó pọ̀ jù nínú ọkọ̀ tí wọ́n ń lò náà, ìdí ni pé ó láyè dáadáa bí Adelua ṣe sọ.
Afurasí mìíràn ni Rotimi Adilola jẹ́wọ́ pé Idimu ni ibùdó àwọn wà tí àwọn ti máa ń pàdé tí wọ́n sì máa ń ti àwọn tí kò bá rí owó san mọ́.
Òmíràn ni Amos Ogunna, ó ní òun ló ni ilé náà tí òun sọ di ayédèrú ilédì fún iṣẹ́ náà, òun kìí bá wọn jáde ó kàn ń yá ikọ̀ náà nílé ni òun ló sì máa ń mójútó àwọn tí wọ́n bá kó wá sí ibẹ̀. Ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún náírà ni owó tirẹ̀ lórí ẹnìkọ̀ọ̀kan tí wọ́n bá mú wá sí ibẹ̀.
Njoku náà jẹ́wọ́ pé ó ti tó ọdún mẹ́jọ tí òun ti ń ṣiṣẹ́ náà ẹni tí àwọn bá sì gbé gbọdọ̀ san owó kó tụn tó ríta. Ẹni ọgọ́ta ọdún ni Njoku báyìí.
Láti ìpínlẹ̀ Akwa-Ibom ni Tina Willy ti wá darapọ̀ mọ́ ikọ̀ yìí, ó ṣe àlàyé pé lẹ́yìn tí ọkọ̀ rẹ̀ kú tí ìyà bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ òun ni ẹ̀gbọ́n òun mú òun wá darapọ̀ mọ́ ikọ̀ náà. Tina rawọ́ ẹ̀bẹ̀ pé kí wọn ó dá òun sílẹ̀, ikú ọkọ òun ló fà á.
Ọ̀kan nínú wọn ti lo oṣù mẹ́rin lẹ́wọ̀n rí lórí ẹ̀sun jìbìtì, òun náà jẹ́ afurasí ikọ̀ one-chance yìí.
Kọmíṣọ́nà Olohundare ṣe ìlérí pé òun yóò mú gbogbo àwọn yòókù tí wọ́n jọ ń ṣe iṣẹ́ yìí, ikọ̀ kan ni wọ́n mú yìí, ó ṣì ku mẹ́fà mìíràn ní abẹ́ Adelua nìkan. Òmíràn nínú wọn gan-an kò gbé ní Èko, wọ́n ń ti ìlú wọn wá ṣe iṣẹ́ náà ni Èkó ni. Ó ní gbogbo wọn ni òun yóò ṣa pátá òun yóò sì ríi pé ètò ààbò Èkó kò mẹ́hẹ.
Àṣeyọrí yìí da bí ti ìgbà tí wọ́n gbé Evans lọ́dún náà lọ́hùn-ún. Ṣé ẹ rántí Evans; ògbólògbó ajínigbé ìgbà náà?
Ó tilẹ̀ rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí ìjọba pé kí wọn ó dá òun sílẹ̀:
Ariwo àti ẹ̀bẹ̀ ló gbẹnu ògbólógbòó ajínigbéṣowó ìlú Èkó tí orúkọ rẹ̀ n jẹ́ Chukwudumeme Onmawadike tí ìnagijẹ rẹ̀ n jẹ́ EVANS kan. Ìgbà kejì rèé tó ti n rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó pé kí wọ́n ṣíjú àànú wo òun, kí òun sì máa lọ láyọ̀ àti àlááfíà nígbà tí ìjọba àpápọ̀ ti fún òun lómínira. Evans ni òun yóò fi ọkọ̀ akóyọyọ mẹ́rínlà ọ̀ṣàrà òun jìnkì àwọn tó ṣàgbákò ìgbèkùn òun lásìkò ìgbà àìmọ̀ rẹ.
Agbẹjọ́rò rẹ ni ó ti ronúpìwàdà báyìí lẹ́yìn ìkẹ́kọ̀ọ́gboyè rẹ̀ lórí ìmọ̀ ẹ̀kọ̣́ ọrọ̀ ajé. O n ràwọ́ ẹ̀bẹ̀ sí ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó kí òun le è má ṣe olùkọ́ fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n ẹgbẹ́ rẹ̀.
Ọ̀gbẹ́ni Chukwudumeme Onmawadike, Evans ni bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀wọ̀n gbére ni ìjọba àpapọ̀ dà fún òun pẹ̀lú ẹ̀sùn ìjínigbéṣowó àti ẹ̀wọ̀n ọdún mérìnlá fún dída omi àlááfíà ìlú rú, wọ́n ti dá òun sílẹ̀ nígbà tí òun ti ronúpìwàdà lọ́gbà ẹ̀wọ̀n.
Evans ní òun ti kẹ́kọ̀ọ́gboyè Olùkọ́ni , òun ti gba ìwé ẹ̀rí (NCE) ti ilé ẹ̀kọ́ gíga tàwọn olùkọ́ni ti ìlú Yewa. Ẹ̀kọ́ nípa ọrọ̀ ajé ni òun kọ́, òún sì yege lọ́dún mẹ́ta ẹ̀kọ́ náà. Evans tún ti n kàwèé síi ní ifáfitì NOUN tí Ààrẹ Olúṣẹgun Ọbásanjọ́ dá á lẹ̀ sí orílẹ̀ èdè Nàìjìríà.
Agbẹjọ́rò rẹ̀ ní kí ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó dá a sílẹ̀ nítorí kí ó le è lọ lo ẹ̀kọ́ àti ìmọ̀ tuntun rẹ̀ fún ànfàáni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.Bí ẹ ò bá gbàgbé, nǹkan bí ọdún díẹ̀ sẹ́yìn ni ọwọ́ pálábá Chukwudumeme Onmawadike tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn mọ̀ si Evans ségi ni ilé rẹ̀ tó wà ni GRA. Ògbólògbó gbọ́mọgbọ́mọ ni ọkùnrin kúkúrú bìlísì yìí, yóò sì pa ẹni tí kò bá le è san iye òbítíbitì owó tí wọn bá bèèrè lọ́wọ́ onítọ̀hún. Iye owó ìtúsílẹ̀ tó le è gbà kéré tán jẹ́ ní mílíọ̀nù náírà.
Ẹgbẹlẹmùkún owó ilẹ̀ wa àti tòkèèrè, kọ́kọ́rọ́ ilé owó lóríṣiríṣi, ìbọn àti oríṣiríṣi nǹkan ni wọ́n bá lákàtà ọ̀daràn yìí. Láti ìgbà náà ló tí n jẹ́jọ́ ìwà láabi náà.
Ìjọba àpapọ̀ ti dáa sílẹ̀ nígbà to ti kẹ́kọ̀ọ́gboyè ṣùgbọ́n kò ṣeéṣe fún un bí ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó kò bá tú okùn lọ́rùn rẹ tán yánányánan. Evans ni kí wọ́n jẹ́ kí òun le è lọ ṣiṣẹ́ olùkọ́ tí orí rán òun





